Ìjọba Nàìjíríà yí ìpinnu rẹ̀ padà lórí àjọ eré ìdárayá bọ́ọ̀lù alápẹ̀rẹ̀ tó bẹ́gilé tẹ́lẹ̀

Oríṣun àwòrán, D'tigers/nigeria basketball
Ijọba orile-ede Naijiria ti yi ìpinnu pada lori ere idaraya gbigbabọọlu sáwọn
lẹyin ti wọn yoo ọwọ ninu ifieyẹ agbaye losu to lọ.
Ajọ to rí sì ere idaraya ati oun to jọ mọ awọn ọdọ lorile-ede Naijiria ni awọn o ni
kopa ninu ifesewonse kankan latari iṣẹlẹ kan to waye ni apa guusu ilẹ adulawo.
Ajọ naa ni ìpinnu awọn ni aṣẹ aarẹ Muhammad Buhari latari igbinyanju ijọba
lati ṣe amujuto ere idaraya naa lati ẹsẹ kuku ati lati ṣe àtúnṣe si.
Iyiyi ìpinnu naa pada waye lẹyin Ipadẹ laarin àjọ agbaye ere gbigbabọọlu sáwọ,
FIBA ati minisita ajọ to rí sì ere idaraya ati oun to jọ mọ awọn ọdọ lorile-ede
Naijiria, Sunday Dare.
Yiyi ìpinnu naa pada túmọ̀ si orile-ede Naijiria yoo ni anfani lati kopa ninu ere
idaraya gbigbabọọlu sáwọn ti Ile adulawo ti yoo waye ni orile-ede Rwanda losu
to bo, nibi ti wọn ti koju Mali, Uganda ati orile-ede Cape Verde. Iko D'Tigers ni o le tente tabili lẹyin ifesewonse akoko ninu oṣu November























