À ń sa ipá wa láti gbógun ti ìgbésùnmọ̀mí - Buhari
Oríṣun àwòrán, Femi Adesina
Ijọba apapọ ti sọ pe oun n sapa oun lati koju fopin si igbesumọ atawọn iwa ọdaran mii ni Naijiria.
Aarẹ Muhammadu Buhari lo sọ ọrọ naa lasiko to n gba lẹta kan lati ọdọ aṣoju ijọba Canada si Naijiria, James Kingston Christoff, ati aṣoju ijọba orilẹ-ede Mexico, Juan Alfred Miranda Oritz, niluu Abuja.
Lasiko to n pe fun ifọwọsowọpọ awọn orilẹ-ede mii lagbaye, Buhari ni ijọba ti ṣe awọn aṣeyọri kan lati koju igbesumọmi pẹlu iranlọwọ awọn orilẹ-ede bii Canada ati Mexico.
Buhari ni “Rogbodiyann to n waye ni Libya ti fi kun awọn eto abo to mẹhẹ lawọn erekusu Afrika atawọn orilẹ-ede mii ni aringbungbun Afrika.”
“Rogbodiyan yii ko yọ Naijiria sẹyin nitori bi a ṣe n koju awọn iwa bii iwa janduku igbesumọmi, ija laarin awọn daran-daran atawọn agbẹ ati bẹẹ bẹẹ lọ.”
“Amọ a ti sẹ awọn aṣeyọri kan lati koju awọn iṣoro eto abo naa pẹlu iranlọwọ awọn orilẹ-ede to jẹ ọrẹ wa bii ti yin bayii lati koju awọn iṣoro naa.”
Buhari tun sọ pe ogun to n waye laarin Russia ati Ukraine ti mu ki ọwọngogo ounjẹ wa lagbaye.
O ni oun gbagbo pe eto ọrọ aje to dẹnukọlẹ lagbaye, to fi mọ ajakalẹ arun Covid-19 naa tun kun awọn iṣoro ti ọpọ orilẹ-ede n dojukọ.
Nibi eto naa, to jẹ ayẹyẹ ikinikaabọ sẹnu iṣẹ tuntun awọn aṣoju orilẹ-ede mejeji naa, Buhari ni ki wọn maṣe yẹsẹ kuro ninu ilana ti awọn aṣaaju wọn fi lelẹ.
Ìròyìn tó ṣe kókó
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ìròyìn tí àwọn ènìyàn fẹ́ràn jùlọ
Content is not available