Tọkọ-tayà Osinbajo kò gbẹ́yìn níbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbi Folu Adeboye
Oríṣun àwòrán, Rccg/twitter
Ìyá Adeboye jẹ́ àwòkọ̀ṣe rere fàwọn obínrin ìwòyí
Igbakeji ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo, tí dáwọ̀ọ́ ìdùnnú pẹ̀lú ìyàwó adari ìjọ ìràpada (Redeemed Christian Church of God), Olusọaguntan Folu Adeboye.
Oríṣun àwòrán, Osinbajo/twitter
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ sí:
Oríṣun àwòrán, Osinbajo/twitter
Osinbajo ní ó jẹ́ ohun ìdunnu lati ni iru arabinrin Folu Adeboye lawujọ àwọn obínrin gẹgẹ bíi oniwàásù àti àwokose fawọn obinrin.
Ó rọ awọn obinrin lati ni suuru pẹ̀lú ẹbí wọn lai faaye gba iwa ipá ninu ile ati lawujọ pẹlu afiwe Iya Adeboye.
O ni àwọn ise ìrànwọ ti Iya Adeboye ń se fawọn ọ̀dọ́ àti àwọn alaini kò lẹ́gbẹ́.
Igbákeji ààrẹ, Ọjọgbọ́n Yemi Osinbajo gbadura kí Ọlọrun túbọ̀ lọ́ra ẹ̀mí wọn
Oríṣun àwòrán, Osibajo/twitter
Arabìnrin Folukẹ Adeboye pe ọmọ ààdọrun ọdún lori oke eèpẹ̀ lánàá.
Opọlọpọ eto ni awọn eniyan ṣe lati fi sami ayẹyẹ ọdun rẹ ti awọn èrò pupọ si n ki olukọ ati oniwaasu naa lori ayelujara kaakiri agbaye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
Ìròyìn tó ṣe kókó
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ìròyìn tí àwọn ènìyàn fẹ́ràn jùlọ
Content is not available