Oyo NLC: A kò bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì láti d'ẹ́rù ba ìjọba tuntun
Ẹgbẹ oṣiṣẹ ijọba nipinlẹ Ọyọ, NLC, ti so iyanṣẹlodi rẹ rọ.
Lasiko to n kede igbesẹ naa, Alaga ẹgbẹ NLC nipinlẹ Ọyọ, Comrade Bayọ Titilọla-Sodo, sọ pe awọn bẹrẹ iyanṣẹlodi pẹlu ireti pe ọjọ diẹ to ku ninu iṣejọba to wa nita lọwọlọwọ nipinlẹ Ọyọ yoo so eso rere fun awọn oṣiṣẹ.
O ni kii ṣe ọna tabi erongba lati dẹru ba ijọba to n bọ.
Lara awọn ohun to fa a ti awọn oṣiṣẹ naa fi yanṣẹlodi gẹgẹ bi Titilọla-Sodo ṣe sọ ni ajẹsilẹ owo oṣu ati owo ifẹhinti awọn oṣiṣẹ fẹhinti, eyi toto ọgọta billiọnu Naira.
Bakan naa ni fifi opin si aṣẹ ti ko jẹ ki wọn o gbe awọn oṣiṣẹ lati ibikan si omii, gbigba awọn oṣiṣẹ ti wsn da duro lọna aitọ pada, ajẹsilẹ owo oṣu awọn olukọ ileewe alakọbẹrẹ ati awsn oṣiṣẹ ijọba ibilẹ kan.
O wa kesi gomina tuntun fun ipinlẹ Ọyọ, Onimọ Erọ Seyi Makinde, pe ko ma ṣe yi ohùn pada lori awọn ileri to ṣe lasiko to n polongo ibo.
Ọjọ Ẹti to kọja ni ẹgbẹ oṣiṣẹ naa bẹrẹ iyanṣẹlodi.
Ìròyìn tó ṣe kókó
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ìròyìn tí àwọn ènìyàn fẹ́ràn jùlọ
Content is not available