2019 Election: Èmi kìí se alárùn ọpọlọ, n kò lọ tọ́jú ara ní Gbagada
Oríṣun àwòrán, Babajide Sanwo-Olu
Olùdíje fún ipò gómìnà fẹ́gbẹ́ òṣèlú APC ní Ìpínlẹ̀ Eko Babajide Sanwo-Olu ti ṣojú abẹ ní kòó lórí ọ̀rọ̀ pé ó ti lọ fún ìtọ́jú ààrun ọpọlọ ni ilé ìwòsàn Ìpínlẹ̀ Eki tó wà ní Gbagada.
Sanwo-Olu ṣàlàyé pé, òun lọ sí ilé ìwòsàn ní Gbagada láti ran àwọn aláìní lọ́wọ́ ni, kìí ṣe wí pé òun lọ tọ́jú ara òun níbẹ̀.
O fìdí ọ̀rọ̀ yìí múlẹ̀ lórí ètò kan láàrọ́ọ̀ Ọjọ́rú lórí ẹ̀rọ amóhùnmáwòrán ní ìlú Eko.
Ẹ rántí pé, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Eko Akinwunmi Ambode nígbà tó bá àwọn oníròyìn sọ̀rọ̀ nínú oṣù kẹsàn án sọ pé, Sanwo-Olu ti lọ ṣètọ́jú ara rẹ̀ rí ní ilé ìwòsàn náà nítorí ó láárùn ọpọlọ rí.
Olùdíje ẹgbẹ́ òsèlú APC àti PDP ń sòkò ọ̀rọ̀ síra wọn
Ojú rèé ìran rèé nílù Èkó bí àwọn olùdíje gbòógì fún gómìnà méjèèjì ṣe ń sòkò ọ̀rọ̀ sí àrà wọn lórí àtẹ̀jíṣẹ́ twitter.
Nínú ọ̀rọ̀ Jìmí Agbaje, ó ní nínú gbogbo ìfọ̀rọ̀wánilẹnuwò tí ó tí ṣe láti ọjọ́ yìí, Babajide Sanwo-Olu kìí gbórí yìn fú àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Eko bíkòse kíí ò máá dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹni tó ń pe ni asujú ẹgbẹ́ tó ó sì máa ń dúpẹ́ fún àànfaní ti wọn fún òun. O fí kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé Sanwo-Olu ò tó bẹ́ẹ̀ láti jade dupò gómìnà ìpínlẹ̀ Eko tíì baa ṣe pe wọn gbe lé àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Eko lórí.
Oríṣun àwòrán, Babjide Sanwo-Olu
Lẹ́yọọ ò sọka náà ní Babajíde ti dálohun , ó ké gbàjare sí àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Eko pe alátako òhún Jimi Agbaje ń gbìyanjú láti dóju ọ̀rọ̀ rú tí ó sì ń gbìyànjú láti fa ọ̀rọ̀ ti kò ní ìtumọ pẹ̀lú lóri ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwo ti òun ṣe níle iṣẹ́ amóhùnmáwòrán kan láàrọ̀ ànàá.
Ìròyìn tó ṣe kókó
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ìròyìn tí àwọn ènìyàn fẹ́ràn jùlọ
Content is not available